Hedayat “A fruitful harvest”
from the gardens of “ Verses and Hadiths ”
Inspiring Dawah cards that highlight the profound meanings of Quranic verses and Prophetic Hadiths. Presented in an accessible and engaging style to help Muslims gain a deeper understanding of their faith with ease.
About Hedayat
Hedayat is a platform that combines simplicity of design and ease of use
displaying the benefits derived from Verses and Hadiths in
attractive cards with unique designs.
Unique Designs
Cards with unique and attractive designs that express the content of the text
Reliable Materials
Scientifically reliable benefits reviewed by a group of scholars
Easy Browsing
You can browse the cards easily and display them effortlessly
Different Languages
Cards are available in more than 40 languages for the benefit of all
Hadith Cards
Lati ọdọ ọmọ ‘Umar – ki Ọlọhun yọnu si awọn mejeeji: Dajudaju Ojiṣẹ Ọlọhun – ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a – ba awọn eeyan sọrọ ni ọjọ ti wọn ṣi Makkah, ni o wa sọ pe: «Mo pe ẹyin eeyan, dajudaju Ọlọhun ti gbe kuro fun yin igberaga igba aimọkan ati ṣiṣe iyanran wọn pẹlu awọn baba wọn, nitori naa meji ni awọn eeyan: eniire olupaya alapọn-ọnle lọdọ Ọlọhun, ati onibajẹ oloriibu ẹni yẹpẹrẹ lọdọ Ọlọhun, awọn eeyan, ọmọ Anabi Aadam ni wọn, ti Ọlọhun si da Aadam lati ibi erupẹ, Ọlọhun sọ pe: {Ẹ̀yin ènìyàn, dájúdájú Àwa ṣẹ̀dá yín láti ara ọkùnrin àti obìnrin. A sì ṣe yín ní orílẹ̀-èdè orílẹ̀-èdè àti ìran-ìran nítorí kí ẹ lè dára yín mọ̀. Dájúdájú alápọ̀n-ọ́nlé jùlọ nínú yín lọ́dọ̀ Allāhu ni ẹni t’ó bẹ̀rù (Rẹ̀) jùlọ. Dájúdájú Allāhu ni Onímọ̀, Alámọ̀tán} [Al-Hujrāt: 13]».
Tirmiziy ni o gba a waAnabi – ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a – ba awọn eeyan sọrọ ni ọjọ ti wọn ṣi Makkah, o wa sọ pe: Mo pe ẹyin eeyan dajudaju Ọlọhun ti gbe kuro fun yin igberaga igba aimọkan ati ijọra-ẹni-loju rẹ, ati fifi awọn baba ẹni ṣe iyanran, ati pe awọn eeyan iran meji ni wọn: Ninu ki o jẹ Mumini eniire olupaya Ọlọhun olutẹle aṣẹ ti n jọ́sìn fun Ọlọhun, eleyii alapọn-ọnle ni lọdọ Ọlọhun, koda ki o ma jẹ ẹni ti o ni ipo ati iran lọdọ awọn eeyan. Tabi ki o jẹ keferi onibajẹ oloriibu, eleyii ẹni yẹpẹrẹ ti ko ni asunsi ni lọdọ Ọlọhun, ti ko si ja mọ nkankan, koda ko jẹ abiyi ti o ni ipo ati ọla. Ati pe gbogbo eeyan pata ọmọ Anabi Aadam ni wọn, ti Ọlọhun si da Aadam lati ibi erupẹ, nitori naa ko lẹtọọ fun ẹni ti ipilẹ rẹ jẹ erupẹ ki o ṣe igberaga ati ijọra-ẹni-loju, ati pe nkan ti o fi idi iyẹn mulẹ ni gbolohun Ọlọhun ti O tobi ti O gbọnngbọn to sọ pe: {Ẹ̀yin ènìyàn, dájúdájú Àwa ṣẹ̀dá yín láti ara ọkùnrin àti obìnrin. A sì ṣe yín ní orílẹ̀-èdè orílẹ̀-èdè àti ìran-ìran nítorí kí ẹ lè dára yín mọ̀. Dájúdájú alápọ̀n-ọ́nlé jùlọ nínú yín lọ́dọ̀ Allāhu ni ẹni t’ó bẹ̀rù (Rẹ̀) jùlọ. Dájúdájú Allāhu ni Onímọ̀, Alámọ̀tán} [Al-Hujrāt: 13].
Lati ọdọ Abu Musa Al-Ash’ariy- ki Ọlọhun yọnu si i- lati ọdọ Anọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- o sọ pe: “Ẹ maa ka Kuraani yii ni ìgbà gbogbo, mo fi Ẹni tí ẹmi Muhammad n bẹ lọ́wọ́ Rẹ bura, o yara sá lọ ju ràkúnmí ninu okùn ti wọn fi dè é lọ”.
Ohun ti wọ́n fi ẹnu kò lé lórí niAnọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- pàṣẹ ki a maa ka Kuraani nígbà gbogbo, ki a si maa tẹra mọ́ kika a ki èèyàn ma baa gbagbe rẹ lẹyin híhá a, o wa tẹnu mọ́ ọn pẹ̀lú ìbúra pe Kuraani yára kuro ninu àyà ju rakunmi ti a so lọ, oun naa ni eyi ti a fi okùn dè ni aarin ẹsẹ, ti eeyan ba n ka a nígbà gbogbo, o maa di i mu, ti o ba si tu u sílẹ̀, o maa lọ.
Lati ọdọ Abu Mas‘ūd – ki Ọlọhun yọnu si i– o sọ pe: Anabi – ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a – sọ pe: «Ẹni ti o ba ka aayah meji ti o gbẹyin Sūratul Bakọra ni oru kan, wọn ti to fún un».
Ohun ti wọ́n fi ẹnu kò lé lórí niAnabi – ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a – sọ wipe dajudaju ẹni tí o ba ka aayah meji ti o gbẹyin Sūratul Bakọra ni alẹ, dajudaju Ọlọhun a to o kuro nibi aburu ati nkan ti ko dáa, wọn tun sọ pe: Yio gbe e nibi didide loru (irun oru), wọn tun sọ pe: Yio gbe e nibi awọn iranti yòókù, wọn tun sọ pe: Dajudaju mejeji ni odiwọn ti o kere ju ti o le to ninu kika Kuraani nibi idide oru (irun oru), wọn si tun sọ nkan ti o yatọ si ìyẹn, ati pe o sunmọ pe gbogbo nkan ti wọn sọ yẹn naa ni o daa ti gbolohun yẹn naa si ko o sinu.
Láti ọ̀dọ̀ Aishah- ki Ọlọhun yọnu si i- pé: Arákùnrin kan jókòó níwájú Anọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- o wa sọ pé: Irẹ ojiṣẹ Ọlọhun, mo ni àwọn ẹrú kan ti wọn maa n pa irọ́ fun mi, wọn tun maa n janba mi, wọn si tun maa n yapa àṣẹ mi, mo maa n bú wọn, mo si maa n lù wọ́n, báwo ni ọ̀rọ̀ mi ati wọn ṣe maa jẹ ni ọdọ Ọlọhun? O sọ pe: “Wọ́n maa ṣírò ijanba ti wọn ṣe fun ẹ, ati bi wọn ṣe yapa àṣẹ rẹ, ati irọ́ ti wọn pa fun ẹ, ati ìyà ti o fi jẹ wọn, tí ìyà ti o fi jẹ wọn ba jẹ odiwọn ẹṣẹ wọn, a jẹ pe o ti ṣe déédéé ara wọn, o o nii ni ẹsan, o o si nii jẹ ìyà, ṣùgbọ́n ti iya ti o fi jẹ wọn ba kere si ẹṣẹ wọn, ìyẹn maa jẹ alekun fun ẹ, ṣùgbọ́n ti iya ti o fi jẹ wọn ba ju ẹṣẹ wọn lọ, wọn maa gba ẹ̀san alekun naa lara rẹ fun wọn”, o sọ pe: Ni arákùnrin naa wa rìn jìnnà, ni o ba bẹ̀rẹ̀ si nii sunkún ti o si n pariwo, ni ojiṣẹ Ọlọhun- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- wa sọ pé: “Ṣe o o ka tira Ọlọhun ti o sọ pe: {A máa gbé àwọn òṣùwọ̀n déédé kalẹ̀ ní Ọjọ́ Àjíǹde. Nítorí náà, wọn kò níí ṣe àbòsí kiní kan fún ẹ̀mí kan}, aaya”, ni arákùnrin naa wa sọ pé: Mo fi Ọlọhun bura irẹ ojiṣẹ Ọlọhun, mi o ri ohun ti o loore fun emi ati awọn ju ki a pínyà lọ, mo n fi ọ jẹ́rìí pe gbogbo wọn ti di olómìnira.
Tirmiziy ni o gba a waArákùnrin kan wa ba Anọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- lati wa fi ẹjọ́ bi àwọn ẹrú rẹ ṣe n hùwà sùn, pe wọn maa n pa irọ́ fun un, wọn si maa n janba rẹ nibi agbafipamọ, wọn si maa n rẹ́ ẹ jẹ nibi ibalopọ, wọn si maa n yapa àṣẹ rẹ, oun naa si maa n bu wọn, o si maa n na wọn lati kọ́ wọn ni ẹ̀kọ́, o wa bi i leere nipa bi ọrọ oun ṣe maa jẹ pẹlu wọn ni Ọjọ́ Àjíǹde? Ni Anọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- wa sọ pé: Wọ́n maa ṣírò ijanba ti wọn ṣe fun ẹ, ati bi wọn ṣe yapa àṣẹ rẹ, ati irọ́ ti wọn pa fun ẹ, ati ìyà ti o fi jẹ wọn, tí ìyà ti o fi jẹ wọn ba jẹ odiwọn ẹṣẹ wọn, o o nii ni ẹsan, o o si nii jẹ ìyà, tí iya ti o fi jẹ wọn ba kere si ẹṣẹ wọn, o maa jẹ alekun ẹsan fun ẹ, ṣùgbọ́n ti iya ti o fi jẹ wọn ba ju ẹṣẹ wọn lọ, wọn maa fi iya jẹ ìwọ naa, wọn si maa gba odiwọn ti o ba le lọ́wọ́ rẹ, wọn si maa fun wọn, ni arákùnrin naa wa rìn jìnnà, o wa bẹ̀rẹ̀ si nii n sunkún ti o si n pariwo, ni ojiṣẹ Ọlọhun- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- wa sọ fún un pé: Ṣé o o ka tira Ọlọhun ti o sọ pe: {A máa gbé àwọn òṣùwọ̀n déédé kalẹ̀ ní Ọjọ́ Àjíǹde. Nítorí náà, wọn kò níí ṣe àbòsí kiní kan fún ẹ̀mí kan. Kí (iṣẹ́) jẹ́ ìwọ̀n èso kardal (bín-íntín), A máa mú un wá. A sì tó ní Olùṣírò} [Al-Anbiyaa: 47], wọn kò níí ṣe àbòsí kiní kan fún ẹni kankan ni Ọjọ́ Àjíǹde, àwọn òṣùwọ̀n si maa wa laarin awọn èèyàn pẹ̀lú déédéé, ni arákùnrin naa wa sọ pé: Mo fi Ọlọhun bura irẹ ojiṣẹ Ọlọhun, mi o ri nǹkan kan ti o ni ọla fun èmi ati awọn ju ki a pínyà lọ, mo n fi ọ jẹ́rìí pe gbogbo wọn ti di ọmọlúwàbí nítorí tí Ọlọhun; ni ti ipaya ìṣirò ati ìyà.
Lati ọdọ Saheed ọmọ Al-Musayyab, láti ọ̀dọ̀ bàbá rẹ, o sọ pé: Nigba ti asiko iku Abu Taalib to, Ojiṣẹ Ọlọhun - ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a - wa ba a, o si ba Abu Jahli ati Abdullāh ọmọ Abu Umayyah ọmọ Mughiirah ni ọdọ rẹ, ni o wa sọ pe: «Irẹ ọmọ-iya baba mi, sọ pe: Laa illaha illā Allāhu, gbolohun kan ni ti maa fi jẹrii gbe ọ ni ọdọ Allāhu», ni Abu Jahli ati Abdullāh ọmọ Abu Umayyah wa sọ pe: Ṣe o fẹ gunri kuro nibi ilana Abdul Mutalibi ni, Ojiṣẹ Ọlọhun - ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a - o si yẹ lẹni ti n fi lọ̀ ọ́ pe ki o wi i, ti awọn mejeeji naa si n paara ọrọ naa, titi ti Abu Taalib fi sọ nkan ti o ba wọn sọ gbẹyin pe: Lori ilana Abdul Mutalibi, ti o si kọ lati sọ: Laa illaha illā Allāhu, o sọ pe: Ojiṣẹ Ọlọhun - ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a - sọ pe: «Mo fi Ọlọhun bura maa maa tọrọ aforijin fun ọ ti wọn o ba ti kọ fun mi kuro nibẹ», ni Ọlọhun wa sọ ọ kalẹ pe: {Kò yẹ fún Ànábì àti àwọn t’ó gbàgbọ́ lódodo láti tọrọ àforíjìn fún àwọn ọ̀sẹbọ} [Al Taobah: 113]. Ni Ọlọhun tun wa sọ ọ kalẹ nipa Abu Taalib, ti O si sọ fun Ojiṣẹ Ọlọhun - ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a - pe ﴾Dájúdájú ìwọ kò lè fi ọ̀nà mọ ẹni tí o fẹ́ràn, ṣùgbọ́n Allāhu l’Ó ń fi ọ̀nà mọ ẹni tí Ó bá fẹ́﴿ [Al Qasas: 56].
Ohun ti wọ́n fi ẹnu kò lé lórí niAnabi - ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a - wọle tọ ọmọ-iya baba rẹ Abu Taalib ti o n pọka iku lọwọ, ni o wa sọ fun un pe: Irẹ ọmọ-iya baba mi, sọ pe "laa ilaaha illa Allāhu", gbolohun kan ti maa fi jẹrii gbe ọ ni ọdọ Allāhu, Ni Abu Jahli ati Abdullāh ọmọ Abu Umayyah wa sọ pe: Irẹ Abu Taalib, ṣe waa fi ilana baba rẹ Abdul Mutalibi silẹ ni? Oun si ni jijọsin fun awọn oriṣa, awọn mejeeji o si yẹ lẹni ti n ba a sọrọ titi ti o fi sọ ọrọ igbẹyin ti o ba wọn sọ pe: Lori ilana Abdul Mutalibi, ilana ẹbọ, ati jijọsin fun awọn oriṣa. Ni Anabi - ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a - wa sọ pe: Maa ṣe adua aforijin fun ọ lopin igba ti Oluwa mi o ba ti kọ fun mi kuro nibẹ, ni gbolohun Ọlọhun ti ọla Rẹ ga ba sọkalẹ pe: {Kò yẹ fún Ànábì àti àwọn t’ó gbàgbọ́ lódodo láti tọrọ àforíjìn fún àwọn ọ̀sẹbọ, wọn ìbáà jẹ́ ẹbí, lẹ́yìn tí ó ti hàn sí wọn pé dájúdájú èrò inú iná Jẹhīm ni wọ́n} [Al Taobah: 113], Ni o wa sọkalẹ nipa Abu Taalib gbolohun Ọlọhun ti ọla Rẹ ga pe: ﴾Dájúdájú ìwọ kò lè fi ọ̀nà mọ ẹni tí o fẹ́ràn, ṣùgbọ́n Allāhu l’Ó ń fi ọ̀nà mọ ẹni tí Ó bá fẹ́. Àti pé Ó nímọ̀ jùlọ nípa àwọn olùmọ̀nà﴿ [Al Qaṣaṣ: 56], Dajudaju oo le fun ẹni ti o ba wu ẹ ni imọna, ati pe nkan ti o jẹ dandan fun ọ ni ki o jiṣẹ, ati pe Ọlọhun ni o máa n fi ẹni ti o ba wu U mọ ọna.
Lati ọdọ Abu Abdir-Rahmaan As-Sulamiy- ki Ọlọhun kẹ́ ẹ- o sọ pe: Awọn ti wọn maa n kọ́ wa bi a ṣe maa ka Kuraani ninu awọn saabe Anọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- sọ fun wa pe àwọn maa n gba aaya mẹ́wàá lọ́dọ̀ ojiṣẹ Ọlọhun- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- àwọn ko nii gba mẹ́wàá miiran titi ti àwọn fi maa mọ imọ ati iṣẹ ti o wa ninu ẹ, wọn sọ pé: A wa kọ́ imọ ati iṣẹ.
Ahmad ni o gba a waAwọn saabe- ki Ọlọhun yọnu si wọn- maa n gba aaya mẹ́wàá lọ́dọ̀ ojiṣẹ Ọlọhun- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- ninu Kuraani, wọn ko si nii bọ si ibòmíràn titi ti wọn fi maa kọ́ imọ ti o wa ninu awọn aaya mẹ́wàá yii ti wọn si maa lò ó, o maa waa ja si pe wọn kọ imọ ati iṣẹ papọ nìyẹn.
Lati ọdọ Az-Zubair ọmọ Al-Awwaam, o sọ pe: Nigba ti (Thumma latus alunna yauma-izin ‘anin na’eem) sọkalẹ (At-Takathur: 8), Az-Zubair sọ pe: Irẹ Ojiṣẹ Ọlọhun, idẹra wo ni wọn maa bi wa leere nipa rẹ, dajudaju mejeeji ni dudu meji, eso dabinu ati omi? O sọ pe: “Oun naa ni o maa jẹ”.
Tirmiziy ni o gba a waNigba ti ayah sọkalẹ: (Thumma latus alunna yauma-izin ‘anin na’eem) o n túmọ̀ si pe: Wọn maa pada beere lọwọ wọn nipa idupẹ lori nnkan ti Ọlọhun ṣe ni idẹra le wọn lori ninu awọn idẹra, Az-Zubair ọmọ Al-‘Awwam- ki Ọlọhun yọnu si i- sọ pe: Irẹ Ojiṣẹ Ọlọhun, idẹra wo ni wọn maa bi wa leere nipa rẹ? Dajudaju idẹra mejeeji ko kii ṣe nnkan ti wọn le bukaata si ibeere ati pe mejeeji ni eso dabinu ati omi! Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- sọ pe: Dajudaju wọn maa bi yin leere nipa idẹra pẹlu isẹsi yii ti ẹ wa nibẹ yìí, nitori pe mejeeji jẹ idẹra nla meji ninu awọn idẹra Ọlọhun- ti ọla Rẹ ga-.
Lati ọdọ Abu Musa Al-ash’ari - ki Ọlọhun yọnu si i - ó sọ pé: Ojiṣẹ Ọlọhun - ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a - sọ pé: “Àpèjúwe Mumini ti n ka Kuraani da gẹgẹ bii èso utrujjah, ti oorun rẹ daa, ti itọwo rẹ naa si daa, àpèjúwe mumini ti kii ka Kuraani da gẹgẹ bii èso dabinu, ti ko ni oorun, ti itọwo rẹ si dùn, àpèjúwe munaafiki ti n ka Kuraani da gẹgẹ bii èso rayhaanah, ti oorun rẹ dùn, ti itọwo rẹ si korò, àpèjúwe munaafiki ti kii ka Kuraani da gẹgẹ bii èso hansọla, ti ko ni oorun, ti itọwo rẹ tún korò".
Ohun ti wọ́n fi ẹnu kò lé lórí niOjiṣẹ Ọlọhun, ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a, ṣe alaye àwọn ìpín awọn eniyan nipa kika Al-Qur’an ati jijẹ anfaani rẹ: Ìpín akọkọ: Mumini ti n ka Kuraani ti o si n ṣe àǹfààní pẹ̀lú rẹ, o da gẹgẹ bii èso utrujjah, ti itọwo ati oorun rẹ daa, ti awọ rẹ si daa, ti anfaani rẹ si pọ̀, o n lo nnkan ti o n ka, o si n ṣe awọn ẹru Ọlọhun ni anfaani. Ìkejì: Mumini ti kii ka Kuraani, o da gẹgẹ bii èso dabinu, itọwo rẹ dun, ko si ni oorun, ọkàn rẹ ko ìgbàgbọ́ sínú, gẹgẹ bi eso dabinu ṣe ko adun sinu nibi itọwo rẹ ati inú rẹ, ati aihan oorun rẹ ti àwọn èèyàn a gbọ́; torí aihan kika rẹ ti awọn eeyan le fi àyà balẹ si gbigbọ rẹ. Ikẹta: Munaafiki ti n ka Kuraani, o da bii eso rayhaanah, ti oorun rẹ daa ti itọwo rẹ korò, torí igbagbọ ko tun ọkàn rẹ ṣe, ko si lo Kuraani, o wa n ṣe bii mumini loju àwọn èèyàn, oorun rẹ ti o daa jọ kika a, itọwo rẹ ti o korò si jọ iṣe Kèfèrí rẹ. Ikẹrin: Munaafiki ti kii ka Kuraani, o da bii eso hansọla, ko ni oorun, itọwo rẹ si korò, àìní oorun rẹ jọ aika rẹ, ìkorò itọwo rẹ jọ ìkorò ìṣe Kèfèrí rẹ, ko si igbagbọ ninu rẹ, òde rẹ naa o ṣe anfaani, bi ko ṣe pe o tun n ko inira bani ni.
Lati ọdọ Ubay ọmọ Kahb- ki Ọlọhun yọnu si i- o sọ pe: Òjíṣẹ́ Ọlọhun- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- sọ pé: “Irẹ Abu Al-Munzir, ǹjẹ́ o mọ aaya wo ninu tira Ọlọhun ti o wa pẹlu rẹ ni o tobi julọ?”, o sọ pe: Mo sọ pé: Ọlọhun ati ojiṣẹ Rẹ ni wọn ni imọ julọ. O sọ pe: “Irẹ Abu Al-Munzir, ǹjẹ́ o mọ aaya wo ninu tira Ọlọhun ti o wa pẹlu rẹ ni o tobi julọ?”, o sọ pe: Mo sọ pé: {Allāhu, kò sí ọlọ́hun kan tí ìjọ́sìn tọ́ sí àfi Òun, Alààyè, Alámòjúútó-ẹ̀dá} [Al-Baqarah: 255]. O sọ pe: O wa fi ọwọ́ lu mi láyà, o wa sọ pé: “Mo fi Ọlọhun búra, o kú oriire imọ naa, ki Ọlọhun ṣe e ni irọrun fun ẹ, irẹ Abu Al-Mundhir”.
Muslim gba a waAnọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- bi Ubay ọmọ Kahb léèrè nipa aaya ti o tobi ju ninu tira Ọlọhun, o wa ṣe iyèméjì nibi dáhùn, lẹ́yìn náà ni o wa sọ pé: Oun ni aayatul Kursiyy: {Allāhu, kò sí ọlọ́hun kan tí ìjọ́sìn tọ́ sí àfi Òun, Alààyè, Alámòjúútó-ẹ̀dá}, Anọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- wa ṣe atilẹyin fun un, Anọbi wa lu u ni àyà lati tọka si pe o kún fun imọ ati ọgbọ́n, o wa ṣe adua fun un pe ki o maa dunnu pẹ̀lú imọ yii ki o si rọrùn fún un.
Láti ọ̀dọ̀ Abu Huraira- ki Ọlọhun yọnu si i- o sọ pe: Awọn Juu ati Kristẹni maa n ka Taoreeta pẹ̀lú èdè Hébérù, wọn si maa n túmọ̀ rẹ pẹlu èdè Lárúbáwá fun awọn Mùsùlùmí, ojiṣẹ Ọlọhun- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- wa sọ pé: “Ẹ má gba ọ̀rọ̀ àwọn Júù àti Kristẹni ni ododo, ẹ si ma pe e ni irọ, ki ẹ sọ pé: {A gbàgbọ́ nínú Allāhu àti ohun tí Wọ́n sọ̀kalẹ̀ fún wa} [Al-Baqarah: 136] Aayah”.
Bukhaariy gba a waAnọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- kilọ fun awọn ìjọ rẹ láti ṣọ́ra fun gbigba ẹtan pẹ̀lú nǹkan ti àwọn Júù àti Kristẹni n gbà wá nínú àwọn ìwé wọn, Níbi tí àwọn Júù ìgbà ayé Ànábì máa ń ka Taoreeta ní èdè Hébérù. Ó jẹ́ èdè àwọn Júù, wọ́n sì túmọ̀ rẹ̀ ní èdè Lárúbáwá, Anọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- wa sọ pé: Ẹ ma gba ọrọ àwọn Júù àti Kristẹni ni ododo, ẹ si ma pe e ni irọ, èyí níbi ohun ti a ko mọ ododo rẹ yatọ si irọ rẹ; Torí pé Ọlọhun ti ọla Rẹ ga pa wa láṣẹ ki a ni igbagbọ ninu Kuraani ati Ìwé ti wọn sọ̀kalẹ̀ fun wọn, ṣùgbọ́n ko si bi a ṣe fẹ mọ èyí tí ó ni àlàáfíà ninu ohun ti wọn n sọ nipa awọn Ìwé sánmọ̀ yẹn yatọ si èyí tí kò ni àlàáfíà; tori ko wa ninu ṣẹria wa ohun ti o maa ṣàlàyé ododo rẹ yatọ si irọ rẹ, Nítorí náà a maa kóra ro, a ko nii gba ọrọ wọn ni ododo; ki a ma baa kópa pẹ̀lú wọn nibi ohun ti wọn yi padà ninu ẹ, a ko si nii pe ọrọ wọn ni irọ; bóyá o le jẹ òdodo, ki a ma baa lọ tako ohun ti wọn pa wa láṣẹ ki a gbagbọ, Anọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- wa pa wa láṣẹ ki a sọ pé: “A gbàgbọ́ nínú Allāhu àti ohun tí Wọ́n sọ̀kalẹ̀ fún wa àti ohun tí Wọ́n sọ̀kalẹ̀ fún (àwọn Ànábì) ’Ibrọ̄hīm, ’Ismọ̄‘īl, ’Ishāƙ, Ya‘ƙūb àti àwọn àrọ́mọdọ́mọ Ya‘ƙūb. (A gbàgbọ́ nínú) ohun tí Wọ́n fún (àwọn Ànábì) Mūsā àti ‘Īsā, àti ohun tí Wọ́n fún àwọn Ànábì (yòókù) láti ọ̀dọ̀ Olúwa wọn. A kò ya ẹnì kan sọ́tọ̀ nínú wọn. Àwa sì ni mùsùlùmí (olùjuwọ́-jusẹ̀ sílẹ̀) fún Un.” [Al-Baqarah: 136].